Láìsí ìmọ́tótó agbègbè àti àyíká wa, nílé, lóko, lọ́nà ìrìn-àjò, kò sí bí a ṣe máa káwọ́ àrùn tàbí àìsàn.

Èyí ló fi dá’ni lójú pé, orílẹ̀-èdè D.R.Y kò ní fi àyè gba ẹnikẹ́ni láti hu ìwà ọ̀bùn tàbí aláìbìkítà fún agbègbè àti àyíká wa ní orílẹ̀-èdè wa yí.

Ìjọba D.R.Y ní ètò tí ó jẹ́ pé ìdọ̀tí, bí ó ti wù kó kéré mọ, kò ní rí ibi fi ṣe ibùjóko ni Orílẹ̀-Èdè Olómìnira Tiwantiwa ti Yorùbá (D.R.Y).

Ẹ jẹ́ kí ìdọ̀tí jìnà sí wà, kí ó sì jìnà sí gbogbo àwùjọ wa káàkiri ilẹ̀ Yorùbá. Orílẹ̀-Èdè D.R.Y kò fi àyè sílẹ̀ fún ìdọ̀tí kankan – fún ààbò ara wa ni.

Yàtọ̀ sí èyí, àyíká tí ó dùn-ún-wò, tí ó sì mọ́ tónítóní, máa njẹ́ ìwúrí fún èèyàn láti ro èrò rere fún ìgbélékè ara wa àti ti orílẹ̀-èdè wa. Ìmọ̀tótó borí àrùn.

The Democratic Republic of the Yoruba also known in the Yoruba history as Yoruba Nation, Yoruba Kingdom, Yoruba Land and Yoruba Country is the newest nation in the world. The 55th nation in Africa and 17th in Western Africa as of 12th April 2024. Yoruba is know a sovereign nation and its no longer part of Nigeria.